“Dajudaju Ọlọhun maa ya arákùnrin kan sọ́tọ̀ nínú ìjọ mi lójú àwọn ẹ̀dá ni ọjọ́ igbende alukiyaamọ
Choose an available translation of this Hadeeth
Hadeeth text
Lati ọdọ Abdullahi ọmọ Amru ọmọ ‘Aas- ki Ọlọhun yọnu si awọn mejeeji- o sọ pe: Ojiṣẹ Ọlọhun- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pé: “Dajudaju Ọlọhun maa ya arákùnrin kan sọ́tọ̀ nínú ìjọ mi lójú àwọn ẹ̀dá ni ọjọ́ igbende alukiyaamọ, O maa ṣí ìwé iṣẹ mọkandinlọgọrun-un fun un, ìwé kọ̀ọ̀kan gùn ni odiwọn ibi tí ojú bá le rína dé, lẹyin naa O maa sọ pé: Ǹjẹ́ nǹkan kan n bẹ nínú eyi ti o fẹ takò? Ǹjẹ́ àwọn malaika òǹkọ̀wé-iṣẹ́ ẹ̀dá ti wọn jẹ oluṣọ ṣe àbòsí rẹ bi? O maa sọ pé: Rara, Irẹ Olúwa mi, O maa sọ pé: Ǹjẹ́ o ni àwíjàre kankan bi? O maa sọ pé: Rárá, Irẹ Oluwa mi, O maa sọ pé: Ko ri bẹẹ, dájúdájú o ni iṣẹ rere kan ni ọdọ Wa; torí pé ko si àbòsí fun ẹ ni oni, wọn maa wa mu iwe pélébé kan jáde ti ohun ti o wa ninu rẹ jẹ: ASH’HADU AN LAA ILAAHA ILLALLOHU, WA ASH’HADU ANNA MUHAMMADAN ABDUHUU WA ROSUULUHUU, O maa sọ pé: Mu òṣùwọ̀n rẹ wá, o maa sọ pé: Irẹ Oluwa mi, iwe pélébé wo ni o wa pẹ̀lú àwọn ìwé iṣẹ yii? O maa sọ pé: Wọn ko nii ṣe abosi fun ọ, o sọ pe: Wọn maa gbe àwọn ìwé iṣẹ naa sórí abọ́ òṣùwọ̀n kan, wọn si maa fi iwe pélébé naa sórí abọ́ òṣùwọ̀n mii, ni àwọn iwe iṣẹ naa maa di ohun ti o fúyẹ́, ti iwe pélébé naa si maa wúwo, ko si nnkan kan ti o le wuwo ju orúkọ Ọlọhun lọ”.
Explanation
Benefits
Sisọ gbolohun: Laa ilaaha illallohu ko tó pẹlu ahọn nikan, bi ko ṣe pe nini imọ nípa ìtumọ̀ rẹ ati ṣíṣe iṣẹ pẹlu nnkan ti o n bèèrè fun jẹ dandan.
Imọkanga ati agbara imu Ọlọhun ni Ọkan ṣoṣo jẹ okùnfà pípa awọn ẹṣẹ rẹ.
Igbagbọ maa n ju ara wọn lọ pẹ̀lú bi ohun ti n bẹ ninu ọkan ba ṣe ju ara lọ nibi imọkanga, awọn kan ninu awọn eniyan a maa sọ gbolohun yii ṣùgbọ́n wọn maa fi iya jẹ wọn ni odiwọn awọn ẹṣẹ wọn.
Attribution
Categories
Share hadeeth
Sharing options · 0 Total shares

