الزلزلة

 

Az-Zalzalah

 

The Earthquake

1 - Az-Zalzalah (The Earthquake) - 001

إِذَا زُلۡزِلَتِ ٱلۡأَرۡضُ زِلۡزَالَهَا
Nígbà tí wọ́n bá mi ilẹ̀ tìtì ní ìmìtìtì rẹ̀,

2 - Az-Zalzalah (The Earthquake) - 002

وَأَخۡرَجَتِ ٱلۡأَرۡضُ أَثۡقَالَهَا
àti (nígbà) tí ilẹ̀ bá tú àwọn ẹrù tó wúwo nínú rẹ̀ jáde,

3 - Az-Zalzalah (The Earthquake) - 003

وَقَالَ ٱلۡإِنسَٰنُ مَا لَهَا
ènìyàn yó sì wí pé: “Kí l’ó mú un?”

4 - Az-Zalzalah (The Earthquake) - 004

يَوۡمَئِذٖ تُحَدِّثُ أَخۡبَارَهَا
Ní ọjọ́ yẹn ni (ilẹ̀) yóò sọ̀rọ̀ nípa àwọn ìró rẹ̀ (tí ẹ̀dá gbé orí ilẹ̀ ṣe).

5 - Az-Zalzalah (The Earthquake) - 005

بِأَنَّ رَبَّكَ أَوۡحَىٰ لَهَا
Nítorí pé dájúdájú Olúwa rẹ l’Ó fún un ní àṣẹ (láti sọ̀rọ̀).

6 - Az-Zalzalah (The Earthquake) - 006

يَوۡمَئِذٖ يَصۡدُرُ ٱلنَّاسُ أَشۡتَاتٗا لِّيُرَوۡاْ أَعۡمَٰلَهُمۡ
Ní ọjọ́ yẹn, àwọn ènìyàn yóò máa gba ọ̀nà ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ lọ nítorí kí wọ́n lè fi àwọn iṣẹ́ wọn hàn wọ́n.

7 - Az-Zalzalah (The Earthquake) - 007

فَمَن يَعۡمَلۡ مِثۡقَالَ ذَرَّةٍ خَيۡرٗا يَرَهُۥ
Nítorí náà, ẹni tí ó bá ṣe iṣẹ́ rere ní òdíwọ̀n ọmọ iná-igún, ó máa rí i.

8 - Az-Zalzalah (The Earthquake) - 008

وَمَن يَعۡمَلۡ مِثۡقَالَ ذَرَّةٖ شَرّٗا يَرَهُۥ
Ẹni tí ó bá sì ṣe iṣẹ́ aburú ní òdíwọ̀n ọmọ iná-igún, ó máa rí i.[1]
1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Wāƙi‘ah; 56:7.

[sc name="verse"][/sc]

Scroll to Top