Ẹru mi da ẹṣẹ kan, o wa sọ pé: Irẹ Ọlọhun, fi orí ẹṣẹ mi jin mi
Choose an available translation of this Hadeeth
Hadeeth text
Láti ọ̀dọ̀ Abu Huraira- ki Ọlọhun yọnu si i-: Lati ọdọ Anọbi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-, ninu nǹkan ti o gba wa lati ọdọ Olúwa rẹ tí Ó lágbára ti O gbọnngbọn, O sọ pe: “Ẹru mi da ẹṣẹ kan, o wa sọ pé: Irẹ Ọlọhun, fi orí ẹṣẹ mi jin mi, Ọlọhun Àlekè-ọla wa sọ pé: Ẹrú Mi da ẹṣẹ kan, o si mọ pe oun ni Olúwa kan ti maa n ṣe àforíjìn ẹṣẹ, ti O si maa n fi iya ẹṣẹ jẹ eeyan, lẹyin naa o tun ṣẹri pada si idi ẹṣẹ, o wa tun sọ pé: Irẹ Oluwa mi, fi ori ẹṣẹ mi jin mi, Ọlọhun ti ọla Rẹ ga tun sọ pé: Ẹrú Mi da ẹṣẹ kan, o si mọ pe oun ni Olúwa kan ti maa n ṣe àforíjìn ẹṣẹ, ti O si maa n fi iya ẹṣẹ jẹ eeyan, lẹyin naa o tun ṣẹri pada si idi ẹṣẹ, o wa tun sọ pé: Irẹ Oluwa mi, fi ori ẹṣẹ mi jin mi, Ọlọhun ti ọla Rẹ ga tun sọ pé: Ẹrú Mi da ẹṣẹ kan, o si mọ pe oun ni Olúwa kan ti maa n ṣe àforíjìn ẹṣẹ, ti O si maa n fi iya ẹṣẹ jẹ eeyan, maa ṣe ohun ti o ba fẹ́, mo ti fi ori jin ọ”.
Explanation
Benefits
Ẹni ti o gbagbọ ninu Ọlọhun maa ni ìrètí amojukuro Olúwa rẹ, o si maa paya ìyà Rẹ̀, yoo waa tètè yára lọ ronupiwada, ko si nii tẹsiwaju nibi ẹṣẹ naa.
Májẹ̀mú ironupiwada ti o ni alaafia ni: Jijawọ kuro nibi ẹṣẹ, ati kika abamọ lori ẹ, ati ìpinnu pe èèyàn ko nii pada sibi ẹṣẹ naa mọ. Tí ìrònúpìwàdà naa ba jẹ kúrò nibi awọn àbòsí ti a ṣe fún awọn èèyàn nipa dúkìá, tabi ọmọlúwàbí, tabi ẹ̀mí, o maa ṣe alekun májẹ̀mú kẹrin, oun naa ni: Bíbọ́ kuro lọwọ ẹni tí ó ni ẹtọ, tabi fifun un ni ẹtọ rẹ.
Pataki imọ nipa Ọlọhun, eyi ti yoo sọ ẹrú di onimimọ nipa awọn alamọri ẹsin rẹ, yoo wa maa ronupiwada nígbàkúùgbà ti o ba ti ṣe àṣìṣe, ko nii sọreti nu, ko si nii tẹsiwaju.
Attribution
Categories
Share hadeeth
Sharing options · 0 Total shares

